Ìpàdé Àpapọ̀ Gbogbogbò
Ètò Àánú Náà
Ìpàdé Àpapọ̀ Gbogbogbò Oṣù Kẹ́rin 2025


11:5

Ètò Àánú Náà

Olúwa jẹ́ aláanú àti pé ètò ìgbàlà ti Baba wa Ọ̀run jẹ́ ètò àánú nítòótọ́.

Ìfipè Kan ti Wòlíì

Ni ọdún tó kọjá níbi ìpàdé àpapọ̀ Oṣù Kẹrin, ní kété lẹ́hìn ìròhìn ayọ̀ pé Ìjọ ti gba Tẹ́mpìlì Kirtland, Ààrẹ Russell M. Nelson pe wá láti ṣe àṣàrò àdúrà ìyàsímímọ́ ti Tẹ́mpìlì Kirtland náà, ti a kọsílẹ̀ nínú ìpín mọ́kàndínàádọ́ọ̀fà ti Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú Àdúrà ìyàsímímọ́ náà, ni Ààrẹ Nelson sọ pé, “ó jẹ́ ìkẹ́kọ̀ọ́ nípa bí tẹ́mpìlì ti nfi agbára fún ẹ̀yin àti èmi níti-ẹ̀mí láti kojú àwọn ìpènijà ìgbésí ayé ní àwọn ọjọ́ ìkẹhìn wọ̀nyí.”

Ó dámi lójú pé ṣíṣe àṣàrò yín nípa ìpín ọgọ́ọ̀rúnlémẹ́ẹ̀sán mú àwọn ìwòye wá tí ó nbùkún yín. Ní àṣálẹ́ yìí, mo pín díẹ̀ nínú àwọn ohun tí mo kọ́ bí mo ti ntẹ̀lé ìfipè wòlíì wa, Ipa ọ̀nà tó nfúnni ní àláfíà sísàlẹ̀ èyítí àṣàrò mi dárí ránmi létí pé Olúwa jẹ́ aláanú àti pé ètò ìgbàlà ti Baba wa Ọ̀run jẹ́ ètò àánú nítòótọ́.

Àwọn Àṣẹṣẹ̀pè Ìránṣẹ́ Ìhìnrere Nsìn nínú Tẹ́mpìlì

Bi ẹ lè ti mọ̀, “àwọn ìránṣẹ́ ìhìnrere àṣẹ̀ṣẹ̀pè ni a ngbà níyànjú láti gba ẹ̀bùn tẹ́mpìlì bí ó bá ti tètè ṣeéṣe tó àti láti lọ sí tẹ́mpìlì léralerá bi àwọn ipò wọn bá ti gbà.” Bí wọ́n bá ti gba ẹ̀bùn tẹ́mpìlì, bákannáà wọ́n “le sìn bíi òṣìṣẹ́ ìlànà kí wọn ó tó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́-ìsìn ìhìnrere.”

Àkókò nínú tẹ́mpìlì ṣaájú wíwọ Ibi Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìránṣẹ́ Ìhìnrere le jẹ́ ìbùkún yíyanilẹ́nu fún àwọn ìránṣẹ́ ìhìnrere titun bí wọ́n ti nkẹ́kọ̀ọ́ síi nípa àwọn májẹ̀mú tẹ́mpìlì ṣaájú pípín àwọn ìbùkún ti àwọn májẹ̀mú náà pẹ̀lú aráyé.

Ṣùgbọ́n nínú ṣíṣe àṣàrò ìpín ọgọ́ọ̀rúnlémẹ́ẹ̀sán, mo kọ́ pé, nínú tẹ́mpìlì, Ọlọ́run nró àwọn ìránṣẹ́ ìhìnrere titun—ní tòótọ́, gbogbo wa—lágbára ní ọ̀nà àfikún, mímọ́ kan. Nínú àdúrà ìyàsímímọ́ náà, tí a fúnni nípa ìfihàn, Jósẹ́fù gbàdúrà pé “nígbàtí àwọn ìránṣẹ́ rẹ yíó bá jáde kúrò nínú ilé rẹ … láti jẹ́ ẹ̀rí nípa orúkọ rẹ,” kí “ọkàn” ti “gbogbo ènìyàn”— ti “àwọn ẹni nlá ilẹ̀ ayé” àti “gbogbo àwọn tálákà, àwọn aláìní, àti awọn [náà] ti a pọ́n lójú … lè di mímú rọ̀.” Ó gbàdúrà pé ki “àwọn ẹ̀tanú le sá kúrò níwájú òtítọ́, àti kí àwọn ènìyàn rẹ le rí ojúrere lójú gbogbo èníyàn; pé kí gbogbo òpin ilẹ̀ ayé le mọ̀ pé àwa, ìránṣẹ́ rẹ, ti gbọ́ ohùn rẹ, àti pé ìwọ ti rán wa.”

Èyí jẹ́ ìlérí rírẹwà fún àṣẹ̀ṣẹ̀pè ìránṣẹ́ ìhìnrere kan—láti jẹ́ kí àwọn ẹ̀tanú “sálọ kúrò níwájú òtítọ́,” láti “rí ojúrere ní ojú gbogbo ènìyàn,” àti láti ríi pé aráyé mọ̀ pé Olúwa ló rán wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wa dájúdájú nílò àwọn ìbùkún kannáà. Yíó ti jẹ́ ìbùkún tó láti rìi kí àwọn ọkàn di rírọ̀ bí a ti nní ìbáṣe pẹ̀lú àwọn aládùúgbò àti alábàáṣiṣẹ́pọ̀. Àdúrà ìyàsímímọ́ náà kò ṣàlàyé ní pàtó bí àkókò wa nínú tẹ́mpìlì yíó ṣe rọ ọkàn awọn ẹlòmíràn, ṣùgbọ́n ó dámi lójú pé ó jẹ́ síso pọ̀ pẹ̀lú bí àkókò nínú ilé Olúwa ti mú àwọn ọ̀kàn tiwa rọ̀ nípa fífi wa lé ààrin Jésù Krístì àti àánú Rẹ̀.

Olúwa Dáhùn Ẹ̀bẹ̀ Joseph Smith fún Àánú

Bí mo ti ṣe àṣàrò àdúrà ìyàsímímọ́ Kirtland, mo ríi bákannáà pé Jósẹ́fù bẹ̀bẹ̀ lẹ́ẹ̀kan àti lẹ́ẹ̀kansíi fún àánú—fún àwọn ọmọ Ìjọ, fún àwọn ọ̀tá Ìjọ, fún àwọn olórí orílẹ̀-èdè náà, fún àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé. Àti, ni ti araẹni gidi, ó bẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú Olúwa láti ránti òun àti láti ṣàánú fún àyànfẹ́ rẹ̀ Emma àti àwọn ọmọ wọn.

Báwo ni ìmọ̀lára Jósẹ́fù gbọ́dọ̀ ti rí nígbàtí, ní ọ̀sẹ̀ kan lẹ́hìnwá, ni òwúrọ̀ ọjọ́ Àjínde, Ọjọ́ Kẹ́ta Oṣù Kẹrin, 1836, nínú Tẹ́mpìlì Kirtland, Olùgbàlà farahàn sí òun àti Oliver Cowdery àti pé, bí a ti kọsílẹ̀ ní ìpín àádọ́ọ̀fà ti Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú, ó wí pé, “Mo ti tẹ́wọ́gba ilé yìí, orúkọ mi yíó sì wà ní ìhín; èmi yíó sì fi ara mi hàn sí àwọn ènìyàn mi nínú àánu nínú ilé yìí.” Ìlérí àánú yìí gbọ́dọ̀ ti ní ìtumọ̀ pàtàkì sí Jósẹ́fù. Àti pé bí Ààrẹ Nelson ti kọ́ni ní Oṣù Kẹrin to kọjá, ìlérí yìí bákannáà “wúlò fún gbogbo tẹ́mpìlì tí a ti yàsímímọ́ lonìí.”

Rírí Àánú nínú Ilé Olúwa

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀nà ló wà nínú èyítí ọ̀kọ̀ọ̀kan wa le rí àánu nínú ilé Olúwa. Èyí ti jẹ́ òtítọ́ láti ìgbà tí Olúwa ti kọ́kọ́ pàṣẹ fún Isráẹ́lì láti kọ́ àgọ́ kan àti láti fi “ìtẹ́ àánu” sí ààrin gbùngbùn rẹ̀. Nínú tẹ́mpìlì, a nrí àánú nínú àwọn májẹ̀mú tí a ndá. Àwọn májẹ̀mú wọnnì, ní àfikún sí májẹ̀mú ti ìrìbọmi, so wá pọ̀ sí Baba àti Ọmọ ó sì nfún wa ní àyè púpọ̀ síi sí ohun ti Ààrẹ Nelson ti kọ́ni pé ó jẹ́ “irú ìfẹ́ àti àánú pàtàkì kan ti a pè ní hessed” ní èdè Hébérù.

A nrí àánú nínú ànfààní láti jẹ́ fífi èdìdi dì pẹ̀lú àwọn ẹbí wa fún ayérayé. A wá nní òye bákannáà pẹ̀lú ṣíṣe kedere púpọ̀ síi pé Ìṣẹ̀dá, Ìṣubú, ẹbọ ètùtù Olùgbàlà, àti agbára wa láti wọlé lẹ́ẹ̀kansíi sí ọ̀dọ̀ Baba wa Ọ̀run—nítòótọ́, gbogbo abala ti ètò ìgbàlà—jẹ́ ìfarahàn ti àánú. Ní tòótọ́, a lè sọ pé ètò ìgbàlà jẹ́ ètò ìdùnnú ní pàtó nítorípé ó jẹ́ ètò àánú.”

Wíwá Ìdáríjì Nṣí Ìlẹ̀kún sí Ẹ̀mí Mímọ́.

Mo ní ìmoore fún ìlérí rírẹwà nínú ìpin àádọ́fà pé Olúwa yíó fi Ara-Rẹ̀ hàn nínú àánu nínú àwọn Tẹ́mpìlì Rẹ̀. Mo ní ìmoore bákannáà fún ohun tí ó fihàn nípa bí Olúwa yíó ti fi Ara-Rẹ̀ hàn nínú àánú nígbàkugbà tí àwa, bíi Jósẹ́fù, bá bẹ̀bẹ̀ fún àánú.

Ẹ̀bẹ̀ Joseph Smith fùn àánú ní ìpín mọ́kàndínlàádọ́fà kìí ṣe ìgbà àkọ́kọ́ tí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ fún àánú mú ìfihàn wá. Nínú Igbó Ṣúúrú Mímọ́, ọ̀dọ́mọdé Joseph gbàdúrà kìí ṣe láti mọ Ìjọ èyí tí ó jẹ́ òtítọ́ nìkan, ṣùgbọ́n ó sọ bákannáà pé òun “kígbe sí Olúwa fún àánú, nítorí kò sí ẹlòmíràn tí mo le tọ̀ lọ láti gba àánú.” Bákannáà dídámọ̀ rẹ̀ pé òun nílò àánú ti Olúwa nìkan le pèsè ìrànlọ́wọ́ láti ṣí àwọn fèrèsé ọ̀run sílẹ̀. Ọdún mẹ́ta lẹ́hìnnáà, angẹ́lì Mórónì farahàn ní títẹ̀lé ohun tí Jósẹ́fù pè ní “àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ òun sí Ọlọ́run Alágbára Jùlọ fún ìdáríjì gbogbo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ àti àwọn àìmọkan mi.”

Irú àpẹrẹ yí ti ìfihàn títẹ̀lé ẹ̀bẹ̀ fún àánú jẹ́ eyítí ó wọ́pọ̀ nínú àwọn ìwé mímọ́. Énósì gbọ́ ohùn Olúwa lẹ́hìn gbígbàdúrà fún ìdáríjì nìkan. Ìyípadà ọkàn ti baba Ọba Lámónì bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú àdúrà pé: “Èmi ó fi gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi sílẹ̀ láti mọ̀ yín.” A lè má jẹ́ bíbùkún pẹ̀lú àwọn ìrírí àrà ọ̀tọ̀ kannáà, ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ntiraka nígbà míràn láti ní ìmọ̀lára àwọn ìdáhùn sí àdúrà, wíwá àánú Olúwa jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọ̀nà alágbára jùlọ láti ní ìmọ̀lára ẹ̀rí ti Ẹmí Mímọ́.

Ríronújinlẹ̀ lórí Àánú Ọlọ́run Nṣí Ìlẹ̀kùn sí Ẹ̀rí kan nípa Ìwé ti Mọ́mọ́nì

Ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ kan tí ó jọra ni a kọ́ni dáradára nínú Mórónì 10:3–5. A máa nfi ìgbà gbogbo ṣe ìkékúrú àwọn ẹsẹ wọ̀nyí láti kọ́ni pé, nípasẹ̀ àdúrà àtọkànwá, a le kọ́ bóyá Ìwé ti Mọ́mọ́nì jẹ́ òtítọ́. Ṣùgbọ́n ìkékúrú yìí le ṣe àìnáání ipa pàtàkì ti àánú. Ẹ fetísí bí Mórónì ti bẹ̀rẹ̀ ìgbani-níyànjú rẹ̀: “Èmi yíò rọ̀ yín pé nígbàtí ẹ̀yin bá kà àwọn ohun wọ̀nyí, … pé ẹyin ó rántí bí Olúwa tí jẹ́ aláànú tó sí àwọn ọmọ ènìyàn, láti igbà ìṣẹ̀dá Ádámù àní títí dé ìgbà tí ẹ̀yin yíò gba àwọn ohun wọ̀nyí, kí ẹ sì rò ó jinlẹ̀ nínú ọkàn yín.”

Mórónì rọ̀ wa kìí ṣe láti ka àwọn ohun wọ̀nyí nìkan—àwọn àkọsílẹ̀ tí òun ti fẹ́ fi èdìdi dì—ṣùgbọ́n bákannáà láti rònú jinlẹ̀ nínú ọkàn wa ohun tí Ìwé ti Mọ́mọ́nì fihàn nípa “bí Olúwa ti jẹ́ aláànú sí àwọn ọmọ ènìyàn sí.” Ríronú jinlẹ̀ lórí àánú Olúwa ni ó nmúra wa sílẹ̀ láti “béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Baba Ayérayé, ní orukọ Krístí, bí àwọn ohun wọ̀nyí kò bá í ṣe òtítọ́.”

Bí a ti nronu jinlẹ̀ lórí Ìwé ti Mọ́mọ́nì, a lè béèrè pé: Njẹ́ ó jẹ́ òtítọ́ gan-an, bí Álmà ti kọ́ni, pé ètò àánú Ọlọ́run fi dáni lójú pé gbogbo ènìyàn ti ó ti gbé rí ní ilẹ̀ ayé yìí ni a ó jí dìde àti pé a ó mú wọn padàbọ̀sípò sí àgọ́ ara pípé wọn? Njẹ́ òtítọ́ ni Ámúlẹ́kì sọ—Njẹ́ àánú Olùgbàlà le tẹ́ gbogbo àwọn ìbéèrè òtítọ́ kíkorò ti àìṣègbè lọ́rùn bíbẹ́ẹ̀kọ́ ìbá jẹ́ dandan fúnwa láti san àti dípò bẹ́ẹ̀ ˆ[ká wa mọ́] nínú apá ààbò”?

Njẹ́ òtítọ́ ni, bí Álmà ti jẹ́rìí, pé Krístì jìyà kìí ṣe fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa nìkan ṣùgbọ́n fún “àwọn ìrora àti àwọn ìpọ́njú wa” kí Òun le “mọ … bí yíó ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú ní ìbámu sí àwọn àìlera wọn”? Njẹ́ Olúwa jẹ́ aláanú tóbẹ́ẹ̀ nítòótọ́, bí Ọba Bẹ́njámínì ti kọ́ni, pé bíi ẹ̀bùn ọ̀fẹ́, Ó ṣe ètùtù “fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wọnnì … tí wọ́n ti kú láì mọ ìfẹ́ Ọlọ́run nípa wọn, tàbí tí wọ́n ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nínú àìmọ̀kan”?

Njẹ́ òtítọ́ ni, bí Léhì ti sọ, pé “Ádámù ṣubú kí ènìyàn le wà; àti pé ènìyàn wà, kí wọn ó le ní ayọ̀”? Àti pé ṣe ó jẹ́ òtítọ́ gan-an, bí Ábínádì ti jẹ́rìí, ní ṣíṣe àyọsọ Isáíàh, pé Jésù Krístì ni a “pa lára fún àwọn ìrékọjá wa, a ṣá a lọ́gbẹ́ fún àwọn àìṣedéédé wa, ìbáwí àláfíà wa nbẹ lára rẹ̀; àti nípa ìnà rẹ̀ ni a mú wa lárada”?

Ní àkótán, Njẹ́ ètò ti Baba bí a ti kọ́ni nínú Ìwé ti Mọ́mọ́nì jẹ́ aláanú báyìí nítòótọ́? Mo jẹ́ ẹ̀rí pé bẹ́ẹ̀ ni àti pé àwọn ìkọ́ni àánú tó nfúnni ní àláfíà àti ìrètí tó wà nínú Ìwé ti Mọ́mọ́nì jẹ́ òtítọ́.

Síbẹ̀, mo wòye pé àwọn kan lè máa tiraka, láìka ìwé kíkà àti àwọn àdúrà ìgbàgbọ́ yín sí, láti mọ ìlérí Mórónì pé Baba Ọ̀run “yíò fi òtítọ́ rẹ̀ hàn sí yín, nípa agbára Ẹ̀mí Mímọ̀.” Mo mọ ìtiraka yìí nítorípé mo mọ̀ ọ́ lára, ní ọdún púpọ̀ sẹ́hìn, nígbàtí àwọn kíkà àkọ́kọ́ mi ti Ìwé ti Mọ́mọ́nì kò mú ìdáhùn ojú-ẹsẹ̀ àti kedere wá sí àwọn àdúrà mi.

Bí o bá ntiraka, njẹ́ kí npè ọ́ láti tẹ̀lé ìmọ̀ràn Mórónì láti ronújinlẹ̀ lórí àwọn ọ̀nà púpọ̀ tí Ìwé ti Mọ́mọ́nì fi nkọ́ni “bí Olúwa ti jẹ́ aláànú tó [si] àwọn ọmọ ènìyàn”? Dá lórí ìrírí mi, mo nírètí pé, nígbàtí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, àláfíà ti Ẹ̀mí Mímọ́ le wọnú ọkàn yín ẹ̀yin sì le mọ̀, gbàgbọ́, kí ẹ sì ní ìmọ̀lára pé Ìwé ti Mọ́mọ́nì àti ètò àánú ti ó nkọ́ni jẹ́ òtítọ́.

Mo fi ìmoore mi hàn fún ètò nlá Baba nípa àánú àti fún ṣíṣetán Olùgbàlà láti gbé e jáde. Mo mọ̀ pé yíó fi Ara-Rẹ̀ hàn nínú àánú nínú àwọn tẹ́mpìlì mímọ́ Rẹ̀ àti ní gbogbo apákan ìgbésí ayé wa bi a bá wá A. Ní orúkọ Jésù Krístì, àmín.

Àwọn Àkọsílẹ̀ ráńpẹ́

  1. Russell M. Nelson, “Ẹ Yọ̀ nínú Ẹ̀bùn àwọn Kọ́kọ́rọ́ Oyè-àlùfáà,” Liahona, May 2024, 121.

  2. Russell M. Nelson, “Ẹ yọ̀ Nínú Ẹ̀bùn àwọn Kọ́kọ́rọ́ Oyè-alùfáà,” 121.

  3. Ìwé-ìléwọ́ Gbogbogbò: Sísìn nínú Ìjọ Jésù Krístì ti àwọn Ènìyàn Mímọ́ Ọjọ́-ìkẹhìn, 24.5.1, Ibi ìkàwé Ìhìnrere.

  4. Bíi ti gbogbo àwọn ìbùkún tẹ́mpìlì, fífúnni Ọlọ́run ní àwọn ìbùkún wọ̀nyí dá lórí pípa àwọn májẹ̀mú wa tí a dá nínú tẹ́mpilì mọ́. Wo Russell M. Nelson, “Ẹ Ṣẹ́gun Ayé kí ẹ sì Rí Ìsinmi,” Làìhónà, Oṣù Kọkànlá 2022, 96: “Ẹnìkọ̀ọ̀kan tí ó ndá àwọn májẹ̀mú … nínú àwọn tẹ́mpìlì—tí ó sì npa wọ́n mọ́—ní ààyè púpọ̀ síi sí agbára ti Jésù Krístì.”

    Bíi àpẹrẹ míràn, ẹ ro ọ̀rọ̀ Àjọ Ààrẹ Kinní nípa wíwọ ẹ̀wù tẹ́mpìlì:“Bí ẹ ti npa àwọn májẹ̀mú yín mọ́pẹ̀lú ànfàní mímọ́ láti wọ ẹ̀wù náà bí a ti kọ́ni nínú àwọn ìlànà ìgbaniwọlé, ẹ ó ní ààyè títóbijù sí àánú, ààbò, okun, àti agbára ti Olùgbàlà. (Ìwé-ìléwọ́ Gbogbogbò, 26.3.3.2; àfikún àtẹnumọ́).

  5. Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 109:55–57.

  6. Wo Russell M. Nelson, “Jésù Krístì Olúwa Yíò Padà Wá,” Làìhónà, Oṣù Kọkànlá 2024, 121–22: “Nihin ni ìlérí mi sí yín: Gbogbo ẹnití ó nwá Jésù Krístì nítòótọ́ yíò rí I nínú tẹ́mpìlì. Ẹ ó ní ìmọ̀lára àánú Rẹ̀.”

  7. Wo Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 109:34: “Ṣàánú fún àwọn ènìyàn yí, àti bí gbogbo ènìyàn ti ṣẹ̀, dáríjì ìrékọjá àwọn ènìyàn rẹ, kí o sì jẹ́ kí wọn ó di píparẹ́ kúrò títíláé.”

  8. Wo Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 109:50.

  9. Wo Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 109:54. Jósẹ́fù béèrè lọ́wọ́ Olúwa bákannáà “láti ṣàánú fún àwọn ọmọ Jákọ́bù, pé kí Jérúsálẹ́mù, láti wákàtí yìí, le bẹ̀rẹ̀sí di ríràpadà; àti kí àjàgà oko ẹrú le bẹ̀rẹ̀ sí di jíjá kúrò ní ilé Dáfídì; àti kí àwọn ọmọ Júdà le bẹ̀rẹ̀ sí padà sí àwọn ilẹ̀ èyítí ìwọ fi fún Ábráhámù, baba wọn” (Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 109:62–64).

  10. Wo Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 109:68.

  11. Wo Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 109:69. Ìwé Ìtúmọ̀ Èdè Òyìnbó ti Oxford ṣe àlàyé àánú bíi “ìkáanú àti ìyọ́nú tí a fihàn sí ẹnìkan tí ó wà nínú ipò àìlágbára kan” (“mercy,” oed.com). Àánú, bíi oore ọ̀fẹ́, jẹ́ àfihàn ìfẹ́ àti inúrere Ọlọ́run— hesed Rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀ àánú fi ojú sùn sórí ṣíṣe ìdádúró ìjìyà tí a yẹ fún, oore ọ̀fẹ́ ní wíwọ́pọ̀ ntọ́ka sí kí Ọlọ́run fúnwa ní àwọn ìbùkún tí a kò yẹ fún àti láìka yíyẹ sí.

  12. Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 110:7.

  13. Nínú ìṣàfihàn àánú ti aràẹni kan, Jósẹ̀fù àti Oliver ni a sọ fún pé, “Ẹ kíyèsíi, a dárí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín; ẹ jẹ́ aláìlèrí ní iwájú mi; nítorínáà, ẹ gbé orí yín sókè kí ẹ sì yọ̀” (Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 110:5).

  14. Russell M. Nelson, “Ẹ yọ̀ Nínú Ẹ̀bùn àwọn Kọ́kọ́rọ́ Oyè-alùfáà,” 119. Ààrẹ Nelson wí pé, “Mo pè yín láti jíròrò ohun tí ìlérí Olúwa túmọ̀sí fún yín nìti-araẹni.”

  15. Wo Ìwé Ìtumọ̀ ti Bíbélì, “Àgọ́”: “Ibi Mímọ́ Jùlọ tí ó gba ẹyọ ohun ẹ̀ṣọ́ kanṣoṣo: Àpótí Májẹ̀mú náà. … Ní orí àpótí náà tí ó sì jẹ́ bíi ìdérí ni ìtẹ́ àánú. Ó nṣiṣẹ́, pẹ̀lú àpótí nísàlẹ̀, bíi pẹpẹ lórí èyítí ètùtù gígajùlọ tí ó jẹ́ mímọ̀ sí òfin àwọn Júù ti njẹ́ ṣíṣe. Lórí rẹ̀ ni wọ́n nwọ́n ẹ̀jẹ̀ ti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Ọjọ́ Ètùtù (Lẹ́fítíkù 16:14–15). Ìtẹ́ àánú náà ni ibi ìfarahàn ogo Ọlọ́run(Ex. 25:22).”

  16. Russell M. Nelson, “Májẹ̀mú Àìlópin Náà,” Liahona, Oṣù Kẹwa 2022, 5. Bí Ààrẹ Nelson ti mú jáde, hesed kò ní èdè òyìnbó kan ní pàtó, ṣùgbọ́n ìyírọ̀padà rẹ̀ tó wọ́pọ̀ nínú Májẹ̀mú Láéláé ni àánú. Nínú ìgbà 248 tí ọ̀rọ̀ náà hesed farahàn nínú Ẹ̀dà ti Ọba Jámèsì ti Májẹ̀mú Láéláé, wọ́n lo àánú ni ìgbà 149, inúrere ní ìgbà 40, àti ìfẹ́-inúrere ní ìgbà 30 (wo Blue Letter Bible, blueletterbible.org/lexicon/h2617/kjv/wlc/0-1/).

  17. Wo Ìwé-ìléwọ́ Gbogbogbò, 72.2. Àpóstélì Jòhánnù kọ́ni pé ẹnikẹ́ni nínú wa kò lè wá sí ọ̀dọ̀ Baba bíkòṣe nípasẹ̀ Olùgbàlà (wo Jòhánnù 14:6 Nínú Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú, Olùgbàlà pèsè àpèjúwe rírẹwà yí nípa ẹ̀bẹ̀ Rẹ̀ fún àánú ní ìgbẹnusọ wa:

    “Fetísílẹ̀ sí i ẹnití ó jẹ́ alágbàwí pẹ̀lú Bàbá, ẹnití ó nbẹ̀bẹ̀ èrò yín níwájú rẹ̀—

    “Wípé: Bàbá, kíyèsí àwọn ìjìyà àti ikú ti ẹni náà tí kò ní ẹ̀ṣẹ̀ rárá, ẹnití inú rẹ dùn sí gidigidi, kíyèsí ẹ̀jẹ̀ Ọmọ rẹ èyí tí a ta sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ ẹni náà tí ìwọ fifúnni kí ìwọ fúnrarẹ lè jẹ́ síṣelógo;

    “Nítorínáà, Baba, dá àwọn arákùnrin mi wọ̀nyí sí tí wọ́n gbàgbọ́ ní orúkọ mi, kí wọ́n lè wá sọ́dọ̀ mi kí wọ́n sì ní ìyè àìnípẹ̀kun” (Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 45:3–5

  18. Ààrẹ Jeffrey R. Holland sọ nígbàkanrí pé: “Dájúdájú ohun tí Ọlọ́run gbádùn jùlọ nípa jíjẹ́ Ọlọ́run ni adùn jíjẹ́ aláànú, pàápàá sí àwọn wọnnì tí wọn kò retí rẹ̀ tí wọ́n sì nfi ìgbà gbogbo ní ìmọ̀lára pé àwọn kò yẹ fún un” (“Àwọn Òṣìṣẹ́ nínú Ọgbà Àjàrà náà,” Lìàhónà, Oṣù Karun 2012, 33). Bákannáà wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 128:19: “Nísisìyí, kínni à ngbọ́ nínú ìhìnrere èyí tí a ti gbà? Ohùn ìdùnnú kan! Ohùn àánú láti ọ̀run; àti ohùn òtítọ́ látinú ilẹ̀-ayé; ìhìn rere ayọ̀ fún àwọn okú; ohùn ti ìdùnnú kan fún àwọn alààyè àti òkú; ìhìn rere ti ayọ̀ nlá. …

  19. Álmà 42:15. Àánu ti nfi ìgbà gbogbo wà ní ààrin gbùngbùn gan-an ti ètò ìgbàlà. Àwọn ìwé mímọ́ mẹ̀ta ni wọ́n ṣeéṣe àpẹrẹ. Néfì parí orí àkọ́kọ́ gan-an ti Ìwé Ti Mọ́mọ́nì nípa wíwípé, “Kíyèsíi, èmi, Néfì, yíò fihàn sí yín pé àánú Olúwa tí ó ní ìtùnú nbẹ lórí gbogbo àwọn ẹni tí ó ti yàn, nítorí ìgbàgbọ́ wọn, láti ṣe wọ́n ní alágbára àní sí agbára ìdásílẹ̀” (1Néfi 1:20).

    Nínú Ẹ́ksódù 34:6Olúwa kéde orúkọ Rẹ̀ fún Mósè bíi “Olúwa Ọlọ́run, aláànú àti oloore-ọ̀fẹ́, onípamọ́ra, àti púpọ̀ ní inúrere àti òtítọ́.” Àwọn kan ti wí pé ẹsẹ yìí lè ti jẹ́ títọ́kasí láti ọwọ́ àwọn wòlíì ìgbà Májẹ̀mú Láéláé ju èyíkéyìí ẹsẹ míràn lọ nínú Májẹ̀mú Láéláé (wo, fún àpẹrẹ, Iṣẹ́ Àkànṣe Bíbélì, “Ẹsẹ tí a Yọsọ Jùlọ nínú Bíbélì,” bibleproject.com/podcast/most-quoted-verse-bible/).

    Nínú Májẹ̀mú Titun, nínú ìwé Lúkù, ẹ rántí pé Sakaráíà ni a mú “yadi, tí kò sì le sọ̀rọ̀” nígbàtí ó ṣiyèméjì ìlérí ángẹ́lì pé Èlísábẹ́tì yíó bí ọmọkùnrin kan nínú ọjọ́ ogbó rẹ̀, ẹnití yíó jẹ́ Jòhánnù Onítẹ̀bọmi (Lúkù 1:20). Nígbàti ohùn Sakaráíà di títú nígbẹ̀hìn, a “kún un fún Ẹ̀mí Mímọ́” àti pé, nínú ìkéde ìta gbangba àkọ́kọ́ pé àkókò fún Mèssíàh ti dé nígbẹ̀hìn, ó “sọtẹ́lẹ̀” pé Olúwa yíó wá “láti ṣe àánú náà tí a ṣèlérí fún àwọn baba wa, àti láti rántí májẹ̀mú mímọ́ rẹ̀; ìbúra èyítí ó búra fún baba wa Ábráhámù” (Lúkù 1:67, 72–73; àfikún àtẹnumọ́).

  20. Àwọn Àròkọ Àkòrí Ìhìnrere, “Àkọsílẹ̀ Ìran Àkọ́kọ́,” Ibi Ìkàwé Ìhìnrere, ní pàtàkì wo àkọsílẹ̀ 1832.

  21. Josefu Smith—ìtàn 1:29. Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 20:5–6 pèsè àpèjúwe mìràn ti ipa ìrònúpìwàdà nínú àwọn ìran alágbára méjì wọ̀nyí. Josefu wí pé “ẹnikẹ́ni kò nílò láti rò pé mo jẹ̀bi àwọn ẹ̀ṣẹ̀ nlá tàbí tí ó léwu,” ṣùgbọ́n ó “ní ìmọ̀lára ìdálẹ́bi fún àwọn àìlera àti àwọn àìpé [rẹ̀]” ó sì nílò ìdáríjì (Joseph Smith—ìtàn 1:28–29

  22. (Wo Énọ́sì 1:1–8.

  23. Álmà 22:18. Àdúrà Álmà pé, “Áà Jésù, ìwọ Ọmọ Ọlọ́run, ṣàánú fún mi,” darí sí ọ̀pọ̀ ìmọ́lẹ̀ àti ìtura kúrò nínú ìrora (wo Álmà 36:17–20). Ààrẹ Jeffrey R. Holland ti sọ nígbàkanrí nípa ẹ̀bẹ̀ Álmà pe: “Bóyá irú àdúrà bẹ́ẹ̀, bíótilẹ̀ kúrú, jẹ́ ìkan pàtàkì jùlọ ti a lè sọ nínú ayé síṣubú kan. Èyíkéyìí àwọn àdúrà míràn ti a ngbà, èyíkéyìí àwọn ìnílò míràn tí a ní, gbogbo wọn padà sí ẹ̀bẹ̀ pé: “Áà Jésù, ìwọ Ọmọ Ọlọ́run, ṣàánú fún mi,” (Our Day Star Rising: Wíwá inú Májẹ̀mú Titun pẹ̀lú Jeffrey R. Holland [2022], 170–71).

  24. Alàgbà Kyle S. McKay kọ́ni dáradára pé, “Ìgbé ayé Jósẹ́fù ní ti ìrònúpìwàdà déédé fúnmi ní ìgbẹkẹ̀lé láti ‘wá pẹ̀lú ìgboyà sí ibi ìtẹ́ oore ọ̀fẹ́ náà, pé kí [èmi] le gba àánú.’” (“Ọkùnrin Náà Ẹnití Ó Sọ̀rọ̀ pẹ̀lú Jèhófàh,” Lìàhónà, Oṣù Kọkànlá 2024, 61).

  25. Mórónì 10:3

  26. Ẹ̀bẹ̀ Mórónì jẹ́ òpinìwé sí ọ̀rọ̀ Néfì ni ìbẹ̀rẹ̀ Ìwé Ti Mọ́mọ́nì gan-an, níbití ó ti sọ èrò tirẹ̀ nínú ìwé kíkọ sí orí àwọn àwo pé: “Ẹ kíyèsíi, èmi, Nífáì, yíò fihàn sí yín pé àánú Olúwa tí ó ní ìtùnú nbẹ lórí gbogbo àwọn ẹni tí ó ti yàn, nítorí ìgbàgbọ́ wọn, láti ṣe wọ́n ní alágbára àní sí agbára ìtúsílẹ̀” (1 Néfì 1:20).

  27. Mórónì 10:4

  28. Wo Mọ́mọ́nì 9:13.

  29. WoÁlmà 40:23: Ẹ̀mí yóò padà sí ara, àti ara sí ọkàn; bẹ́ẹ̀ni, àti gbogbo ẹsẹ̀ àti ìsẹ́po ni aó dá padà sí ara rẹ̀; nítòótọ́, àni irun orí kan kì yio sọnù; ṣùgbọ́n ohun gbogbo ni aó múpadàbọ̀sípò sí ipò dídára àti pípé rẹ̀.”

  30. Álmà 34:16. Bí a ti ngbèrò bi Olúwa ti ṣe jẹ́ aláànú sí, a lè fẹ́ jẹ́ dídánwò láti yọ àánú kúrò lára òdodo—láti rò pé àánú ìfẹ́ni ti Baba wa Ọ̀run nìkan le borí òdodo. Ṣùgbọ́n bí Álmà ti kọ́ni pé, “ètò àánú náà kò lè wáyé bíkòṣepé a ṣe ètùtù kan; nítorínáà, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ṣe ètùtù fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ aráyé, láti mú ètò àánú náà wáyé, láti ṣe ìtánràn fún ẹ̀tọ́ àìṣègbè, kí Ọlọ́run lè jẹ́ Ọlọ́run pípé, títọ́, àti Ọlọ́run aláànú bákannáà” (Álmà 42:15; àfikún àtẹnumọ́).

    Gbogbo ìfẹ́ Olùgbàlà fún wa tó kún fún àánú kò lè gbà wá là. Dípò bẹ́ẹ̀, ó jẹ́ ìjìyà Rẹ̀ ni ìbéèrè àìṣègbè tòótọ́ gan-an àti tó kún fún ìrora ni ó ngbà wá là. Ní tòótọ́, èyí kò dín pàtàkì ìfẹ́ Rẹ̀ kù. Dájúdájú, ìfẹ́ Rẹ̀ fún wa—àti ìfẹ́ inú Rẹ̀ láti ṣe ìfẹ́ ti Baba, ẹnití ó fẹ́ràn wa bákannáà—ni ó mú kí Òun ó ṣetán láti jìyà (wo Jòhánnù 3:16; Ẹkọ àti Àwọn Májẹmú 34:3). Ṣùgbọ́n ìfẹ́ nìkan kò lè ṣiṣẹ́.

    Nígbàmíràn, a lè fojúsùn sórí ìfẹ́ Rẹ̀ fún wa gẹ́gẹ́ bí àwa ti wà tóbẹ́ẹ̀ tí a ó sọ ìríran nù ní ti òtítọ́ pé bí a ti wà—bíi ọkùnrin áti obìnrin ẹlẹ́ran ara ẹnití ìhùwàsí rẹ̀ láìleyẹ̀ ti kùnà gbígbé nínú àwọn òfin—béèrè pé kí àìṣègbè jẹ́ títẹ́lọ́rùn. Bí a bá ṣi òye ní ti a sì wo ìfẹ́ Rẹ̀ bíi jíju ìbéèrè àìṣègbè nù, a dín ẹ̀bùn ẹbọ ọrẹ ètùtù rẹ̀ kù àti ìjìyà tí Ó ṣe láti san gbèsè òdodo. Yíó jẹ́ ẹ̀dà ohun ìrẹ̀wẹ̀sì bí a bá ní òye ìfẹ́ Rẹ̀ fún wa pé ó jẹ́ láti sọ ẹbọ ọrẹ ètutù Rẹ̀ di àìpọn-dandan. Ó ti jẹ́ dídárajù tó láti fi ojúkojú wo ìbéèrè àìṣègbè náà ni kíkún, àti nígbànáà kí a dúpẹ́ pé Ó fẹ́ràn wa tóbẹ́ẹ̀ láti gbé àwọn ìbéèrè toótọ́ gan-an wọnnì nítorí wa.

  31. Álmà 7:11–12.

  32. Mòsíàh 3:11.

  33. 2 Néfì 2:25.

  34. Mòsíàh 14:5.

  35. Mórónì 10:4.

  36. Mórónì 10:3.

  37. Ààrẹ M. Russell Ballard gbà wá níyànjú láti sọ ẹ̀rí “ohun tí o mọ̀ àti tí o gbàgbọ́ àti ohun tí o mọ̀lára” (“Ẹ Ránti Ohun Tó Ṣe Pàtàkì Jùlọ,” Lìàhónà, Oṣù Karun 2023, 107).

  38. Ní sísọ àbá yí, èmi kò níi lọ́kàn láti sọ “fọ́múlà” ìrọ́pò kan fún ẹ̀rí ti jíjẹ́ òtítọ́ Ìwé Ti Mọ́mọ́nì tàbí ìhìnrere. Bí Alàgbà David A. Bednar ti kọ́ni, ìfihàn le wá bíi “ìmọ́lẹ̀ kan tí a tàn nínú yàrá tó ṣókùnkùn,” níbiti ìfihàn náà ti jẹ́ gbígbà “kíákíá, pátápátá àti gbogbo rẹ̀ lẹ́ẹ̀kannáà.” Ó le wá bákannáà bíi “ìmọ́lẹ̀ tó npọ̀ síi díẹ̀díẹ̀ tó ntàn láti inú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn, … ìlà lórí ìlà, ẹsẹ lórí ẹsẹ (2 Néfì 28:30 Irú ìbánisọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ láti ọ́dọ́ Baba Ọ̀run díẹ̀díẹ̀ àti jẹ́ẹ́jẹ́ ‘nkán sí orí [ọkàn wa] bíi àwọn ìrì láti ọ̀run’ (Ẹkọ àti Àwọn Májẹmú 121:45 Irú àwòrán ìfihàn yí dàbí pé ó wọ́pọ̀ ju ṣíṣe ọ̀wọ́n lọ” (“Ẹ̀mi Ìfihàn Náà,” Lìàhónà, Oṣù Karun 2011, 88).