“Jésù Krístì: Ìrètí àti Ìlèrí Àjínde,” Làìhónà, Apr. 2025.
Ọ̀rọ̀ Oṣooṣù Làìhónà Oṣù Kẹ́rin 2025
Jésù Krístì: Ìrètí àti Ìlérí Àjínde
Nípasẹ̀ Ìrètí àti Ìlérí Àjínde, Jésù Krístì kún àwọn òngbẹ ọkàn wa ó sì dáhun àwọn ìbéèrè ọkàn wa.
Àwọn Ìjúwe nípasẹ̀ Michael Dunford
Ẹ jọ̀wọ́ ẹ dà àkókò ìdákẹ́jẹ́ àti ààyè ibi mímọ́ ti ẹ̀mí kan sílẹ̀ bí ẹ ṣe nka ọ̀rọ yi.
Lọ́pọ̀ ìgbà, ayé wa ní ariwo, tí ó kún fún ẹ̀tàn àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n nígbàtí a bá wà ní ṣíṣi, òtítọ́, àti aláìléwu pẹ̀lú ara wa àti Ọlọ́run, Ìrètí àti Ìlérí Ọdún Àjínde nínú Jésù Krístì di gidi. Ní irú àwọn àkókò bẹ́ẹ̀, a bẹ̀bẹ̀:
“Báwo ni mo ṣe le rí ọmọ ẹbí mi, ọ̀rẹ́ mi, olólùfẹ́ mi lẹ́ẹ̀kansíi?”
“Nínú ayé kan ti ìyára-lemọ́lemọ́ ‘mo yan ara mi’ àwọn ìbáṣepọ̀, níbo ni èmi ó ti rí tí èmi ó sì ní ìmọ̀lára àláfíà, ìrètí, àti ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run (wo Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 107:19), àwọn tí ó yí mi ká, àti èmi fúnra mi?”
“Ǹjẹ́ ẹnìkan wà tí mo lè nífẹ̀ẹ́—tí yíò sì ní ìfẹ́ mi lódodo? Njẹ́ àwọn ìbáṣepọ̀ májẹ̀mú le dàgbà kí ó sì pẹ́, kìí ṣe bí ìtàn àròsọ ṣùgbọ́n pẹ̀lú àwọn ìsopọ̀ tí ó lágbára ju àwọn okùn ikú lọ, ayọ̀ nítòótọ́ àti láéláé?”
“Níbití ìrora, ijìyà, àti àìṣodo púpọ̀ wa, báwo ni a ṣe le dásí àláfíà, ìṣọ̀kan, àti òye nínú Jésú Krístì àti ìhìnrere àti Ìjọ Rẹ̀ tí a múpadàbọ̀sípò?”
Ní àkókò Ọdún Àjínde yí, mo pín ẹ̀ri mi nípa Jésù Krístì àti Ìlérí àti Ìrètí Rẹ̀.
Ìlérí Májẹ̀mú Ti Jíjẹ́ àti Ìdí
Ọlọ́run, Baba wa Ayérayé ní Ọ̀run; Jésù Krístì, Àyànfẹ́ Ọmọ Rẹ̀; àti Ẹmí Mímọ́ súnmọ́ wa fúnra wọn. Ìmọ́lẹ̀ àìlópin ayérayé wọn, àánú, àti ìfẹ́ ìràpadà ti wà ní ìdàpọ̀ nínú ìdì ìṣẹ̀dá àti aṣọ ìwàláyé wa (wo Álmà 30:44; Mósè6:62–63).
Nínú Ìgbìmọ̀ Ìṣáájú ní Ọ̀run, “àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ kọrin papọ̀, àti pé gbogbo àwọn ọmọkùnrin [àti àwọn ọmọbìnrin] ti Ọlọ́run sì hó fún ayọ̀” (Jobu 38:7). A yan àṣàyàn. Bayi a rìn nípa ìgbàgbọ́. Nípasẹ̀ ìrírí tiwa fúnra wa, a ṣàwárí ẹ̀wà tí Ọlọ́run ṣèlérí, wípé, ayọ̀, àti ète nínú àwọn àìní-ìdánilójú, ìrẹ̀wẹ̀sì, àti àwọn ìpèníjà.
A ko pinnu làti rìn káàkiri nìkan ní àíní -ìdalójú ìwàláyé. A lè bá ọ̀run sọ̀rọ̀, kọ́ ìgbàgbọ́ àti wíwà nínú ẹbí àti nínú ìdílé àti ìletò àwọn Ènìyàn Mímọ́, kí a sì di olóòtọ́ jùlọ, òmìnira jùlọ, ojúlówó jùlọ, ara ẹni aláyọ̀ nípasẹ̀ ìmúratán àti ìgbọràn aláyọ̀ sí àwọn òfin Ọlọ́run. Ètùtù—è-tù-tù—nínú àti nípasẹ̀ Jésù Krístì mú májẹ̀mú wíwà pẹ̀lú.
Ìrètí ti Ìgbèsì-Ayé Jésù Krístì àti Iṣẹ́ ìhìnrere
Ní ojojúmọ́, ìrètí àti ìlérí Àjíǹde pẹ̀lú àwọn ìbùkún àti ẹ̀kọ́ tí Jésù Krístì pín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ pípé Rẹ̀. Tì a ti yàn láti ìpinlẹ̀ṣẹ̀, Jésù Krístì nìkan ni a bí ní Ọmọ Bíbí Kanṣoṣo ti Ọlọ́run (wo Jákọ́bù 4:5; Álmà 12:33–34; Mósè 5:7, 9). Ó dàgbà nínú ọgbọ́n àti ìdàgbà, ó rí ojú rere lọ́dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn (wo Lúkù 2:52). Ní wíwá nìkan láti ṣe ìfẹ́ Bàbá Rẹ̀, Jésù Kristi dárí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ jì, ó wo àìlera sàn, ó jí àwọn òkú dìde, ó sì tu àwọn aláìsàn àti àwọn tí ó dá nìkan wà nínú.
Lẹ́ẹ̀kan, lẹ́hìn ìgbààwẹ̀ ogóji ọjọ́, Ó jẹri, “Ẹ̀mí Olúwa nbẹ lára mi, nítorí ó ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìhìnrere fún àwọn òtòṣì; ó ti rán mi láti ṣe ìwòsàn oníròbìnújẹ́ ọkàn, láti wàásù ìtúsílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn, àti ìríran fún àwọn afọ́jú, láti tú àwọn tí a palára sílẹ̀ ní òmìnira” (Lúkù 4:18; bákannáà wo Ìsàíàh 61:1).
Èyíinì ni olukúlùkù wa.
Ní Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn, Jésù Krístì wẹ ẹsẹ̀ àwọn ọmọ ẹ̀hìn Rẹ̀ (wo Jòhánnù 13:4–8). Nínú méjèèjí Ayé Àtijọ́ àti Titun, náà “omi ìyè” àti “oúnjẹ ìyè” Tìkárarẹ̀ dá sákrámẹ́ntì sílẹ̀. Nínú ìlàna mímọ́ sákrámẹ́ntì, a képe orúkọ Baba a sì dá májẹ̀mú láti gba orukọ Jésù Krístì sóri wa, rántí Rẹ̀ nígbàgbogbo, kí a sì pa àwọn òfin Rẹ̀ mọ́, kí a lé ní Ẹ̀mí Rẹ̀ pẹ̀lú wa nígbàgbogbo (wo Lúkù 22:19–20; 3 Néfì 18:7, 10–11).
Nínú Ọgbà Gẹ́tsémánè, Jésù jìyà ju bí ènìyàn ṣe lè jìyà láti ràpadà àti láti ṣe ètùtù fún wa. Ẹ̀jẹ̀ wa láti gbogbo ihò ara. Ó jìyà ìrora wọ̀nyí fún gbogbo ènìyàn, kí a má bàa jìyà bí a bá ronúpìwàdà (wo Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 18:11; 19:16).
Ní dídà àti ní fífi ẹ̀sùn èké kàn àn, wọ́n fi Jésù Kristi ṣe yẹ̀yẹ́ wọ́n sì náà, wọ́n sì fi adé ẹ̀gún lé orí ìrẹ̀lẹ̀ Rẹ̀ (wo Máttéù 27:26, 29; Markù 15:15, 17, 20, 31; Lúkù 22:63; Jòhánnù 19:1–2). “A pa á lára nítorí àiṣédédé wa … pẹ̀lú àwọn pàṣán rẹ̀ a mú wa láradá” (Isáíàh 53:5). A “gbé e sókè lórí àgbélébú” láti fà wá sọ́dọ̀ Rẹ̀ (wo 3 Néfì 27:14–15). Síbẹ̀, páàpàá lórí àgbélébu, Jésù Krístì dáríjì (wo Lúkù 23:34). Ó sọ fún Jòhánnù láti tọ́jú ìyá Rẹ̀ (wo Jòhánnù 19:26–27). Ó nímọ̀lára ìkọ̀sílẹ̀ (wo Máttéù 27:46; Markù 15:34). Kí ìwé mímọ́ náà le ṣẹ, Ó sọ pé òùngbẹ ngbẹ Òun (wo Jòhánnù 19:28). Nígbàtí a parí ohun gbogbo, Òun Tìkárarẹ̀ “jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀” (Lúkù 23:46; wo pẹ̀lú Jòhánnù 10:17–18).
Jésù Krístì mọ bó ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ nínú àwọn àìsàn, àìlera, ìdánìkanwà, ìyapa, àti ìnira wa (wo Àlmá 7:12). Irú àwọn ìpọ́njú bẹ́ẹ̀ sábà máa nwá gẹ́gẹ́bí àbájáde yíyàn àwọn ẹlòmíràn. Ó tún mọ bí a ṣe lè bá wa yọ̀ nínú ìdùnnú àti ìmoore wa, bí a ṣe lè sunkún pẹ̀lú wa nígbà tí ayọ̀ wa bá kún. Ní inútútù, Ó pè wá ní orúkọ Rẹ̀, nípa ohùn Rẹ̀, sínú agbo Rẹ̀. Ó pe gbogbo ènìyàn níbi gbogbo. Ó pè wa láti rí i àti láti lóye ìgbésí-ayé ikú nípasẹ̀ ìrísí ayérayé. Bí a ṣe nrìn ní ìdúróṣinṣin tí a sì npa àwọn májẹ̀mú wa mọ́, Ó ṣèlérí pé ohun gbogbo lè ṣiṣẹ́ papọ̀ fún ire wa (wo Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 90:24; Rómù 8:28).
Ní àkókò àti ọ̀nà Rẹ̀, ìmúpadàbọ̀sípò wá—kì í ṣe bí àwọn nǹkan ṣe rí nìkan ṣùgbọ́n sí ohun tí wọ́n lè dà pẹ̀lú. Lòótọ́, Jésù Kristi lè dá wa sílẹ̀ lọ́wọ́ ìgbèkùn àti ẹ̀ṣẹ̀, lọ́wọ́ ikú àti ọ̀run àpáàdì, ó sì lè ràn wá lọ́wọ́ láti mú ìdánimọ̀ àtọ̀runwá wa ṣẹ bí a ti ndi púpọ̀ ju bí a ti rò lọ, nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ àti ìrònúpìwàdà.
Ìléri ti Ìgbàlà
Nítorí ti Jésù Krístì, ikú kì í ṣe òpin. Ní ọjọ́ Àjínde a kéde:
Nípa àṣẹ àti agbára láti ọ̀dọ̀ baba Rẹ̀, Jésù lè fi ẹ̀mí Rẹ̀ lélẹ̀ kí ó sì tún gbé e sókè (wo Jòhánnù 10:17). Nígbàtí ara rẹ̀ dùbúlẹ̀ nínú ibojì, Jésù Kristi ṣe ìránṣẹ́, ó sì ṣètò rẹ̀ nínú ayé àwọn ẹ̀mí, ní pípólongo “ìràpadà wọn kúrò nínú ìdè ikú” (Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 138:16).
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kẹta, Ó dìde láti inú ibojì náà. Ó bá Màríà sọ̀rọ̀. Ó farahan àwọn ọmọ ẹ̀yìn méjì ní ojú ọ̀nà Emmausi, Àwọn Àpọ́sítélì Rẹ̀, àti àwọn mìíràn. (Wo Máttéù 28; Markù 16; Lúkù 24; Jòhánnù 20.)
Ninu ẹ̀rí chiasmatic, O pe awọn ọmọ-ẹhin Rẹ̀ lati sọ àwọ̀n wọn si ìha keji ọkọ̀; ní àkókò yìí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó tún kún fún ẹja, àwọn àwọ̀n náà kò já (wo Jòhánnù 21:6–11; Lúkù 5:3–7). Ó bọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ó sì bẹ Peteru lẹ́ẹ̀mẹta péré pé kí ó bọ́ àwọn àgùtàn òun ati àwọn ọ̀dọ́-àgùtàn (see Jòhánnù 21:12–17). Ó gòkè re ọ̀run, ó sì ń kéde pe àwọn ọmọ ẹ̀hìn Rẹ̀ nígbà náà àti gbogbo wa nísisìyí láti ṣe àjọpín ìhìn iṣẹ́ ológo Àjíǹde àti ìhìnrere Rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo orílẹ̀-èdè, ìbátan, àti ènìyàn (wo Máttéù 28:19–20; Markù 16:15).
Jésù Krístì ni Olùṣọ́-àgùtàn rere àti Ọ̀dọ́-àgùtàn Ọlọ́run. Ó fi ẹ̀mí Rẹ̀ fun, ó sì fi ẹ̀mí Rẹ̀ fún, àwọn àgùtàn Rẹ̀. Nínú ọgbà àti lórí àgbélébu, Ó ru ohun tí kò lè faradà ósì ṣe ètùtù fún wa. Ní àkókò àti ayérayé, Ó fi àpẹrẹ hàn wá bí “ikú ṣe ṣí ọ̀nà àbáwọlé sínú ayérayé.”
Nípasẹ̀ agbára Ètùtù àti Àjíǹde Krístì, ara àti ẹ̀mí wa yíò tún padà ní àjíǹde ti ara. Àwa yíò jẹ́ ológo, tún padàbọ̀sípò ní ojú àti férémù ti ara, ẹsẹ̀ sí ẹsẹ̀. Àní àwọn irun orí wa yíò tún padàbọ̀sípò. Àwa yíò jẹ́ òmìnira lọ́wọ́ àwọn àìlera ti àkókò, àìsàn, ìjàmbá ti ara, àti àìlágbára ọpọlọ. Ètùtu Krístì le bùkún wa láti borí gbogbo irú ìyapa ti ẹ̀mí àti ikú ti ẹ̀mi. Ní ipò ìrònúpìwàdà, a ní òmìnira kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ áti ìbànújẹ́ tí a sì ṣí sí ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìfẹ́ àti ayọ̀ ayérayé. Mímọ́, mọ́, òmìnira, a lè padà nínú ìbátan ẹbí wa tí a ní ọ̀wọ̀ jù lọ sí ògo, wíwà ní ọ̀run ti Ọlọ́run Bàbá wa àti Jésù Kristi.
Àwa yíò tún rí àwọn olólùfẹ́ wa lẹ́ẹ̀kansí i. Nigbàtí a bá tún darapọ̀ mọ́ àwọn wọ̀nnì tí a nifẹ, àwa yíò rí ara wa pẹ̀lú ojú ìwòye ayérayé—pẹ̀lú ìfẹ́ nlá, òye, àti inúrere. Ètùtù Jésù Kristi lè ràn wá lọ́wọ́ láti rántí ohun tó ṣe pàtàkì kí á sì gbàgbé ohun tí kò ṣe é. Rírí Olùgbàlà àti àwọn ìbáṣepọ̀ wa pẹ̀lú ìgbàgbọ́ àti ọpẹ́ ti ó tóbi jùlọ nmú àláfíà wa, gbé àwọn ẹrù wùwo, mú àwọn ọkàn làjà, àti ìṣọ̀kan àwọn ẹbí ní àkókò àti ayérayé.
Ìrètí Ọ̀pọ̀ àti Ayọ̀
Ọdún Àjínde nínú Jésù Krístì pẹ̀lú ṣíṣi fèrèsé ọ̀run sílẹ̀, èso-àjàrà npọ̀ sí i, àti pé àwọn ilẹ̀ ndi alárinrin. Ọdún àjínde nínú Jésù Krístì pẹ̀lú ìtùnú àti ìtọ́jú àwọn opó àti àwọn ọmọ aláìníbaba, àwọn tí ebi npa àti aláìnírànlọ́wọ́, àwọn tí ẹ̀rù nbà, àwọn tí a lò nílòkulò, tàbí àwọn aláìmọ̀kan tí a mú ní ọ̀nà ìpalára. Lọ́kan ti ẹnìkọ̀ọ̀kan, Jésù Krístì npè wa láti rí i àti láti ṣe ìrànṣẹ́ pẹ̀lú ìfẹ́ àti àánú, gẹ́gẹ́bí Ó ti ṣe.
Nínú ohun rere gbogbo, Jésù Krístì mú padàbọ̀sípò lọ́pọ̀lọpọ̀ (wo Jòhánnù 10:10; Àlmà 40:20–24). Ó ṣè àwọn ìlérí pé “ilẹ̀ ayé kún, ó sì tó àti láti dá sí” (Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 104:17). Ìmúpadàbọ̀sípò àwọn ohun gbogbo pẹ̀lú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìhìnrere Rẹ̀, àṣẹ àti agbára oyè-àlùfáà Rẹ̀, àti àwọn ìlànà mímọ́ àti àwọn májẹ̀mú tí a rí nínú Ìjọ Rẹ̀, tí a pè ní orúkọ̀ Rẹ̀, àní Ìjọ Jésù Krístì ti àwọn Ènìyàn Mímọ́ Ọjọ́-ìkẹhìn.
Ọdún àjínde Jésù Krístì pẹ̀lú àwọn ilé mímọ́ Olúwa síi ti ó nsúnmọ́ àwọn ọmọ Ọlọ́run síi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ibi, tí ó nmú ẹ̀kọ́ ti “àwọn olùgbàlà lórí Òkè Síónì wá sínu ọkan wa” (wo Obadíàh 1:21). Olúwa pèsè ọ̀nà ìsọdimímọ́, àìmọtara-ẹni-nìkan fún wa láti rúbọ lórí ilẹ̀ ayé ohun tí àwọn olólùfẹ́ wọn tí wọ́n ti kú nílò tí wọ́n sì ní ìfẹ́-ọkàn ní ayérayé tí wọn kò lè rí gbà fún arawọn
Irú bẹ́ẹ̀ ni ìrètí mi, ìlérí, àti ẹ̀rí. Mo jẹ́ ẹ̀ri Ọlọ́run Baba wa; Olùgbàlà àti Olùràpadà wa, Jésù Krístì; àti Ẹmí Mímọ́ náà. Ní Ọdún Àjíǹde àti lójojúmọ́, ẹ jẹ́ kí a rí ìrètí ayérayé àti ìlérí nínú ètò ìdùnnú Ọlọ́run, pẹ̀lú ipa ọ̀nà májẹ̀mú rẹ̀ nípa ìyípadà àtọ̀runwá láti inú ikú sí àìleèkú àti ìyè àìnípẹ̀kun. Lójojúmọ́ kí ìdánilójú Ètùtù Jésù Krístì gbé ẹrù wa sókè, ràn wá lọ́wọ́ láti tu àwọn ẹlòmíràn nínú nínú ìbànújẹ́ wọn, kí a sì dá ọkàn wa sílẹ̀ láti gba ayọ̀ rẹ̀ ní kíkún.
Nípasẹ̀ Ìrètí àti Ìlérí Àjínde, Jésù Krístì kún àwọn òngbẹ ọkàn wa ó sì dáhun àwọn ìbéèrè ọkàn wa.
© 2025 nípasẹ̀ Intellectual Reserve, Inc. Gbogbo àwọn ẹ̀tọ́ ní a pamọ́. A tẹ̀ẹ́ ní USA. Àṣẹ Èdè Gẹ̀ẹ́sì: 6/19. Àṣẹ Ìyírọ̀padà: 6/19. Ìyírọ̀padà-èdè ti Ọ̀rọ Osoòṣù Lìàhónà, April 2025. Yoruba. 19612 779