Fríẹ́ndì
Ádámù àti Éfà
Fríẹ́ndì Oṣù Kínní 2026


“Ádámù àti Éfà,” Fríẹ́ndì, Oṣù Kínní 2026, 46–48.

Àwọn Ọ̀rọ̀ Oṣooṣù Fríẹ́ndì , Oṣù Kínní 2026

Ádámù àti Éfà

Ádámù àti Éfà nínú Ọgbà Édénì pẹ̀lú àwọn ẹranko

Ádámù àti Éfà ni àkọ́kọ́ lára àwọn ọmọ Ọlọ́run láti wá sí ayé. Wọ́n gbé nínú Ọgbà Édẹ́nì.

Igi ìyè

Ọlọ́run jẹ́kí wọ́n jẹ èso gbogbo igi ṣùgbọ́n ọ̀kan. Bí wọ́n bá jẹ lára igi ìmọ̀ rere àti ibi, wọn yíò ní láti fi ọgba sílẹ̀ kí wọ́n sì kú nígbẹ̀hìn. Ṣùgbọ́n Sátánì purọ́ fún wọn. Ó wípé bí wọ́n bá jẹ èso, wọn yíò mọ rere kúrò nínú ibi ṣùgbọ́n wọn kò ní kú.

Éfà nmú èso lára igi ìmọ̀ rere àti ibi

Éfà yàn láti jẹ èso náà.

Ọwọ́ Éfà nnà èso náà sí ọwọ́ Ádámù

Nígbànáà ó fún Ádámù lára èso náà Ó tún yàn láti jẹ ẹ́.

Ádámù àti Éfà nfi ara pamọ́ nínú igbó nígbàtí Baba Ọ̀run àti Jésù Krístì farahàn

Ọlọ́run àti Jésù Krístì bẹ̀ wọ́n wò, ṣùgbọ́n Ádámù àti Éfà bẹ̀rù wọ́n sì sápamọ́. Ọlọ́run bèèrè bí wọ́n bá ti jẹ èso láti ara igi náà.

Ádámù àti Éfà wọ kóòtù awọ wọ́n sì nfi Ọgbà Édẹ́nì sílẹ̀

Ádámù àti Éfà wípé wọ́n jẹ́ èso. Nísisìyí wọ́n ní láti fi Ọgbà Édẹ́nì sílẹ̀. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ní ètò kan fún wọn. Nisisìyí wọ́n mọ títọ́ kúrò nínú àṣìṣe wọ́n sì lè bí àwọn ọmọ.

Ádámù àti Éfà pẹ̀lú ẹbí wọn

Ádámù àti Éfà ṣe ìlérí láti gbọ́ran sí àwọn òfin Ọlọ́run. Wọ́n kọ́ díẹ síi nípa Ọmọ Ọlọ́run, Jésù Krístì. Wọ́n ní inúdídùn nítorí Òun yíò ràn ẹbí wọ́n lọ́wọ́ láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.

Ojú-ewé Kíkùn

Jésù Dá Ayé

Ojú-ewé PDF

Ìjúwe láti ọwọ́ Audrey Day

Kíni àwọn ohun dídùnmọ́ni jùlọ yín tí Jésù Krístì dá?