2025
Lucy Wá Àwọn Òtítọ́ náà rí
Oṣù Kẹrin 2025


“Lucy Wá Àwọn Òtítọ́ náà rí,” Frẹ́ndì, Oṣù Kẹrin 2025, 26–28.

Ọ̀rọ̀ Oṣooṣù Frẹ́ndì Oṣù Kẹ́rin, 2025

Lucy Wá Àwọn Òtítọ́ náà rí

Ọ̀dọ́mọbìrin kan nṣí ilẹ̀kùn láti jẹ́kí ẹgbẹ́ àwọn ọkùnrin kan wọlé nígbàtí obìrin kan jóko ní lúùmù kan

Ní ọjọ́ kan, Lucy Morley ọmọ-ọdún-márundínlógún nran aládúùgbò rẹ̀, Abigail Daniels, lọ́wọ́ láti hun aṣọ. Bí wọ́n ṣe nṣiṣẹ́, àwọn missínárì mẹ́ta kanlẹ̀kùn. Wọ́n sọ wípé Jésù Krístì ni ó rán wọn láti pín ọ̀rọ̀ kan.

Obìnrin tí ó jóko ní lúùmù fajúro nígbàtí àwọn ọkùnrin nbá ọmọdébìrin náà sọ̀rọ̀

Àwọn ọkùnrin náà sọ fún Abigail àti Lucy pé Jésù ti pe Joseph Smith láti jẹ́ wòlíì. Wọ́n sọ fún wọn bákannáà nípa Ìwé ti Mọ́mọ́nì.

Obìnrin tó nbínú nlé àwọn ọkùnrin jáde kúrò nínú ilé rẹ̀

Ó ya Lucy lẹ́nu pé, Abigail bínú. Ó mú kí àwọn òjíṣẹ́ ìhìnrere náà kúrò.

Àwọn ọkùnrin bojú wẹ̀hìn bí ọmọbìnrin ṣe nsáré tẹ̀lé wọn

Lucy mọ̀ pé ìránṣẹ́ Ọlọ́run ni àwọn òjíṣẹ́ ìhìnrere náà jẹ́. Ó sọ fún wọn pé kí wọ́n bẹ ẹbí òun wò lójú ọ̀nà.

Àwọn ọkùnrin ní tábìlì oúnjẹ àṣálẹ́ pẹ̀lú ọmọbìnrin àti ẹbí rẹ̀

Àwọn òjíṣẹ́ ìhìnrere náà lọ sí ilé Morley. Àwọn òbí Lucy pe àwọn òjíṣẹ́ ìhìnrere náà láti kọ́ wọn àti àwọn ọ̀rẹ́ wọn.

Ọmọbìrin tí ó sì nfi aṣọ sí èjìká obìnrin nígbàtí ẹlòmíràn nṣe ìribọmi ní odò kan ní abẹ́lẹ̀

Lálẹ́ ọjọ́ náà, ènìyàn mẹ́tàdínlógún ló ṣe ìrìbọmi. Ní àwọn ọjọ́ méèlo kan síi, lílé ní àádọ́ta ènìyàn gbọ́ àwọn òjíṣẹ́ ìhìnrere wọ́n sì ṣe ìrìbọmi. Àní Abigail aládúùgbò Lucy yí èrò rẹ̀ padà. Òun àti ọkọ rẹ̀, lẹgbẹ pẹ̀lú Lucy àti àwọn ọmọ ẹbí rẹ̀, yàn láti tẹ̀lé Jésù Krístì nípa ṣíṣe ìrìbọmi.

Ojú-ewé Kíkùn

Nítorí Jésù Krístì, Èmi Yíò Jínde

Ìlà-àwòrán ibojì tó ṣófo

ìjúwe láti ọwọ́ Corey Egbert

Báwo ni ẹ ṣe nrántí Jésù ní akokò Ọdún Àjínde?